Aare egbe àwọn
olorin fuji nígbà kan, Alhaji Saka Ayinde Odunsi ẹni tàwọn èèyàn
tún mo sì Saka Orobo tí ṣàpèjúwe
Ọba Oniru, Alayeluwa Oba Idowu
Abiodun gege bí òpó ńlá kán to wo nílé Yoruba lójijì, táwọn èèyàn kò ní í
gbàgbé láéláé.
Orobo nínú ọ̀rọ̀ ẹ sọ pé,
títí láyé ni iran
Yoruba ati Nigeria lapapo yóò máa rántí ipa manigbagbe tí Ọba Oniru kò laarin ọmọ
adarihunrun
Ó fi kún un pé ilosiwaju rere ti Kabiyesi náà mú bá ìlú e,
Eti-Osa, ipinle Eko lapapo kò ṣe fowo
ro seyin rárá, bẹ́ẹ̀ ni àjọṣepo to dán moran to ni pẹ̀lú àwọn ọba
alayé akẹgbẹ́ e ko sai mú eto àlàáfíà to dara wá ní gbogbo
àgbègbè ẹ àtàwọn íbi tó sún mọ́ ọn.
Lára àwọn ohun
iwuri tí Kabiyesi yìí ṣe nígbà
ayé ẹ ní eto ilé kiko lọ́nà ìgbàlódé sì Oniru estate ni
Victoria Island, l"Ekoo èyí tó mú ìlú e rẹwà gidi, tó sì sọ ó di
apewaawo lágbègbè ohun."
Saka Orobo, olorin fuji |
Orobo nínú ọ̀rọ̀ ẹ sọ pé
"Mo ń fi asiko yii sedaro pelu awon molebi Ọba Óniru, àwọn aráàlú lori ikú Oba wá, Alayeluwa Oba Idowu Abiodun Oniru.
Ikaya ńlá ni ikú ohun je sugbon a dúpẹ́ wí pé isẹmi tó
dara ni wọn lo, bẹẹ ni wọn fi igbe ayé wọn ṣe
òpòlopò èèyàn looore kí Olúwa bá wa ké wọn, kò
fi wọn sì àlùjonna onidera.
“Nígbà ayé wọn, bàbà
dáadáa ní wón, tí ilé àti ona wọn gba
gbogbo èèyàn, ìdùnnú àti àlàáfíà ni Ọba
Idowu Abiodun Oniru máa ń wà fún gbogbo ènìyàn, èyí tó mú un yàtò
púpò, tí àwọn èèyàn sì máa ń rí í
gege bíi bába gbogbo ìlú "
Odun 1937, ní wón bí Oba Idowu Abiodun Oniru, ọjọ́ Aje
Monde ose yìí ni Kabiyesi ohun jáde láyé léni ọdún mejilelogorin.
0 Comments