GBAJUMO

CORONA VIRUS: OMOTAYEBI OLORIN ISLAM SUN AYEYE E SIWAJU

Bi opo eeyan se n mura lati ba gbajumo olorin esin Islam nni, Alhaja Aminat Babalola seye nla to maa n se lodoodun, iyen OMOTAYEBI DAY,  ni bayii, o ti sun ayeye ohun siwaju.
Ninu atejade to fi sita lo ti so pe, “Mo fe fi asiko yii so fun gbogbo eyin ololufe wa wi pe ayeye OMOTAYEBI DAY ta a ti kede e wi pe yoo waye lopin ose yii ko ni i see se lasiko yii latara ofin konile-o-gbele ti ijoba kede e. A fe fi da yin loju wi pe ni kete ti ijoba ba ti  aisan buruku yii, CORONA VIRUS ba ti kase nile, lojuese naa la o fi asiko ti ayeye ohun yoo waye sita.”
Sannde to n bo yii lo ti kede tele wi pe ayeye naa yoo waye ni Time Square, n’Ikeja l’Ekoo, sugbon wahala aisan CORONA VIRUS to gbode kan yii lo mu un fagile na, to n si reti igba ti ijoba yoo so pe ajakale arun ohun ti kase nile.
Okan lara awon olorin esin Islam to lami-laka daadaa ni Alhaja Aminat Babalola eni tawon eeyan tun mo si Omotayebi.  Lodoodun lo maa n sayeye ohun, lati odun to koja naa lo ti kede wi pe, oun yoo se todun yii lona to yato, bee lawon ololufe e kaakiri agbaye ti fokan si i pe, asiwaju awon olorin Musulumi lobinrin yii yoo se bebe lodun yii.
Egbe kan wa ni Nigeria yii, awon olorin Musulumi lo ni in, ISMAN loruko re n je, Omotayebi yii si ni Amira won, eyi to tumo si Asaaju lobinrin.


Post a Comment

0 Comments