![]() |
Jumoke Okoya-Thomas |
Aṣaaju
awọn
obinrin ninu ẹgbẹ
oṣelu
APC nipinlẹ
Eko, Ọnarebu
Jumokẹ
Ọkọya-Thomas
ti sọ
fun awọn
agba ẹgbẹ
naa pe ki wọn
kilọ
fun Oloye Kẹmi
Nelson to jẹ
olori awọn
obinrin fẹgbẹ
oṣelu
ọhun
nilẹ
Yoruba.
O ni ki wọn
kilọ
fobinrin naa ko dẹkun
lati maa kan oun labuku tabi yẹyẹ
oun nita gbangba, nitoro ki i ṣe pe oun naa ko mọ
nnkan to yẹ
ki oun
ṣe
fun un.
O sọrọ
yii ninu atẹjade
to fi ranṣẹ
sawọn
oniroyin. O ni gbogbo abuku tobinrin naa fi n kan oun latigba toun ti depo aṣaaju
awọn
obinrin fun ẹgbẹ
oṣelu
APC lati inu oṣu
karun-un ti
to gẹ bayii.
Ninu atẹjade
naa lo ti so pe, ‘Eyi ni lati jẹ
kawọn
araalu mọ
nipa iwa ainitiju ti Oloye Kẹmi Nelson n hu, to fi
n ko abuku ba Ọnarebu
Jumọkẹ
Ọkọya-Thomas.
Lọjọ
Aje, Monde, ọjọ
kẹtadinlọgbọn,
oṣu
kẹjọ
ni Kẹmi
Nelson atawọn
tọọgi
mẹfa
ja wọ
ọfiisi
alaga wa, iyẹn
Ọnarebu
Tunde Balogun nigba ta a wa ninu ipade oloye ẹgbẹ.
![]() |
Kemi Nelson |
O fi kun un pe nise ni ọkan
lara awọn
tọọgi
obinrin naa, Ayọ
Alli Balogun sọ
foun loju awọn
oloye ẹgbẹ
yooku pe oun yoo foju oun ri mabo.
O ni, kaka koun fun un lesi, ṣe
loun jade ninu ọfiisi
alaga naa, ṣugbọn
siyalẹnu
oun, niṣe
ni tọọgi naa
lọ
ba amugbalẹgbẹ
oun, Alaaja Abiọdun to
si doju ija kọ
ọ
debi pe wọn
sare gbe obinrin naa lọ si ọsibitu
nibi to ti lo gba itọju.
Jumọke
Ọkọya-Thomas
tun sọ
ninu atẹjade
naa pe gbogbo ọna
loun gba lati fi nawọ
ifẹ
si Kẹmi
Nelson ṣugbọn
ti gbogbo rẹ
ja si pabo
O ti wa rọ
awọn
agba ẹgbẹ
naa pe ki wọn
pe Kemi Nelson nibi ti wọn ti le ba a sọrọ,
ki wọn
si kilọ
fun un pe ko jawọ
ninu gbogbo iwa radarada ti obinrin naa hu ti ko yẹ
ki won maa ba a nibẹ
pẹlu
ipo to wa. O ni, idaamu ti o n fun oun
ti fẹ
ga ju ẹmi
oun lọ
bayii, bee lo ti
fẹ maa ṣakoba
fawọn
iṣẹ
to wa niwaju oun.
Bakan naa lo fi kun un pe nnkan
ti ẹgbẹ
oṣelu
APC nilo lakooko yii ni isọkan lati le fi koju ibo to n bọ
lọna.
Bee
lo tun gba awọn
alatilẹyin
ẹ
niyanju lati gba alaafia laaye laarin ara won ki wọn
si jọ
maa wa bi ẹgbẹ
naa yoo ṣe
bori ninu ibo to n bọ
lọna
naa.
0 Comments